Play all audios:
SUNDAY IGBOHO: ''Ẹ Ó RÍJÀ OBA, TÍ Ẹ BÁ GBÌYÀNJÚ LÁTI FỌ́WỌ́ KAN SUNDAY IGBOHO'' 21 Ẹrẹ̀nà 2021 AJIJAGBARA ILẸ YORUBA, ỌGBẸNI SUNDAY ADEYEMO TI ỌPỌ MỌ SI SUNDAY IGBOHO
TUN TI KILỌ FAWỌN TO BA N GBERO LATI MU UN. Nigba ti Igboho ṣe abẹwo si Oba ilu Oke-Iho lagbegbe Oke Ogun nipinlẹ Oyo, Oba Rafiu Osuolale Mustapha, Igboho sọ pe Alaafin Oyo, Oba Lamidi
Olayiwola Adeyemi duro gbọin-gbọin lẹyin ohun. Igboho sọ ninu fido kan to fi sori Facebook pe ''nigba tawọn ijọba Naijiria lọ ba Alaafin wi pe ko fa Sunday Igboho le wọn lọwọ, o ni
ko ṣeeṣe bẹẹ. * Kò sí Oduduwa Nation kankan ni ilẹ̀ Iwo! Kí n má gbọ́ ọ - Oluwo * Àwọn tó jí Oba Imope l'Ogun yìnbọn fún ọlọ́dẹ, Olorí ní ẹbí kábíyèsí kò ní N200M tí wọ́n ń béèrè *
'Èmi Alake yóò bi àwọn alálẹ̀ ilẹ̀ àtàwọn Ogboni ná bí mo bá tilẹ̀ máa tako Sunday Igboho ámbọ̀sìbọ́sí...' * Ẹyọ kan lára agbára tí mo ní, ni mo lò láti mú Wakili - Gani Adams *
Ǹkan pàtàkì márùn-ún tí gbogbo obìnrin tó ní ojú ara gbọ́dọ̀ mọ̀ * Ìyàtọ tàbí àfiwé wo ló wà láàrin Sunday Igboho, Nnamdi Kanu àti Asari Dokubo? Alaafin ni Sunday Igboho ti ẹ n wo yẹn, mẹwaa
ni, eleyi ti ẹ n ri yẹn to n kaakiri kii ṣe Sunday Igboho tori pe oun mọ an dele dele. Nitoripe awọn baba toun atawọn baba tiẹ jọ ṣe pọ ni. Skip Èyítí A Ń Kà Jùlọ and continue reading ÈYÍTÍ
A Ń KÀ JÙLỌ * Afurasí agbébọn ṣíná ìbọn bolẹ̀ nílé ẹ̀kọ́ girama, èèyàn mẹ́wàá kú * Bàbá ẹni odun 68 torí fóònù kó sí kọ̀ǹga ní Ibadan * Aráàlú tú sí ìgboro lẹ́yìn tí ẹni tó bú ọ̀gá ọlọ́pàá
lójú òpó X kú sí àtìmọ́lé * Àbọ̀ ìwádìí UN rèé lórí ìdì tí àwón èèyàn kò ṣe fẹ́ ẹ́ bí ọmọ púpọ̀ mọ́ ní Naijiria End of Èyítí A Ń Kà Jùlọ Ti ẹ ba si gbiyanju lati fọwọ kan Sunday Igboho, igba
naa lẹ o rija ọba, Alaafin lo sọ bẹẹ. Alaafin lo kọkọ kọ lẹta si Buhari pe o to gẹẹ nipa ọrọ awọn Fulani nipinlẹ Oyo,'' Igboho lo sọ bẹẹ. Sunday Igboho ko ṣai sọ fun Oba Mustapha
pe oun ṣetan lati le awọn Fulani kuro lori ilẹ Oke-Iho ti Kabiyesi ba fẹ bẹẹ. Igboho tun sọ fun Kabiyesi nipa erongba rẹ lori bi iran Yoruba yoo ti yapa kuro lara Naijiria. Ajijagbara Igboho
ni yiyapa iran Yoruba kuro lara Naijiria ti ṣeeṣe na. Ninu ọrọ tirẹ, Oba Mustapha Adeitan Keji gbadura pe fun Igboho pe didaduro iran Yoruba yoo ṣeeṣe.